البلد
The City • 20 ayahs • Meccan
بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ
1Èmi (Allāhu) ń fi ìlú yìí[1] búra.
2Ìwọ sì ní ẹ̀tọ́ sí ìlú yìí (láti jagun nínú rẹ̀).[1]
3Èmi (Allāhu) ń fi òbí àti ohun tó bí búra.
4Dájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn sínú ìṣòro.
5Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò ní agbára lórí òun ni?
6Ó (sì) ń wí pé: “Èmi ti bàná dúkìá ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (láti fi tako Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -)”
7Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò rí òun ni?
8Ṣé A kò ṣe ojú méjì fún un?
9Àti ahọ́n pẹ̀lú ètè méjì (tí A ṣe fún un)?
10A sì fi ọ̀nà méjì mọ̀ ọ́n.
11Kò sì lọ rin ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí níbi Iná!
12Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí?
13(Òhun ni) títú ẹrú sílẹ̀ lóko ẹrú.
14Tàbí fífún ènìyàn ní oúnjẹ ní ọjọ́ ebi.
15(Ẹ lè fún) ọmọ-òrukàn nínú ẹbí,
16tàbí mẹ̀kúnnù tí kò ní gá tí kò ní go (olòṣì paraku).
17Lẹ́yìn náà, kí ó wà nínú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ń gbara wọn níyànjú sùúrù ṣíṣe, tí wọ́n sì tún ń gbara wọn níyànjú àánú ṣíṣe.
18Àwọn wọ̀nyẹn ni èrò ọwọ́ ọ̀tún.
19Àwọn tó sì ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Wa, àwọn ni èrò ọwọ́ òsì.[1]
20Wọ́n máa ti àwọn ìlẹ̀kùn Iná pa mọ́ wọn lórí pátápátá.