At-Tariq

الطارق

The Night Comer17 ayahsMeccan

بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ

وَٱلسَّمَآءِ وَٱلطَّارِقِ﴿١

1(Allāhu) fi sánmọ̀ àti Tọ̄riƙ búra.

وَمَآ أَدۡرَىٰكَ مَا ٱلطَّارِقُ﴿٢

2Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Tọ̄riƙ?

ٱلنَّجۡمُ ٱلثَّاقِبُ﴿٣

3Ìràwọ̀ tí ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ń tàn ròrò (ní alẹ́ ni).

إِن كُلُّ نَفۡسٖ لَّمَّا عَلَيۡهَا حَافِظٞ﴿٤

4Kò sí ẹ̀mí kan àfi kí ẹ̀ṣọ́ kan wà fún un (nínú àwọn mọlāika).

فَلۡيَنظُرِ ٱلۡإِنسَٰنُ مِمَّ خُلِقَ﴿٥

5Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí ohun tí A fi ṣẹ̀dá rẹ̀.

خُلِقَ مِن مَّآءٖ دَافِقٖ﴿٦

6Wọ́n ṣẹ̀dá rẹ̀ láti inú omi tó ń tú jáde kọ̀ọ́kọ̀ọ́.

يَخۡرُجُ مِنۢ بَيۡنِ ٱلصُّلۡبِ وَٱلتَّرَآئِبِ﴿٧

7Ó ń jáde láti ààrin ìbàdí ọkùnrin àti àwọn ẹfọ́nhà igbá-àyà obìnrin.

إِنَّهُۥ عَلَىٰ رَجۡعِهِۦ لَقَادِرٞ﴿٨

8Dájúdájú Allāhu ni Alágbára lóri ìdápadà rẹ̀

يَوۡمَ تُبۡلَى ٱلسَّرَآئِرُ﴿٩

9ní ọjọ́ tí wọ́n máa ṣe àyẹ̀wò àwọn (iṣẹ́) àṣepamọ́.

فَمَا لَهُۥ مِن قُوَّةٖ وَلَا نَاصِرٖ﴿١٠

10Nígbà náà, kò níí sí agbára tàbí alárànṣe kan fún un.

وَٱلسَّمَآءِ ذَاتِ ٱلرَّجۡعِ﴿١١

11Allāhu fi sánmọ̀ tó ń rọ òjò ní ọdọọdún búra.

وَٱلۡأَرۡضِ ذَاتِ ٱلصَّدۡعِ﴿١٢

12Ó tún fi ilẹ̀ tó ń sán kànkàn (fún híhùjáde èso) búra.

إِنَّهُۥ لَقَوۡلٞ فَصۡلٞ﴿١٣

13Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ọ̀rọ̀-ìpínyà (láààrin òdodo àti irọ́).

وَمَا هُوَ بِٱلۡهَزۡلِ﴿١٤

14Kì í sì ṣe àwàdà.

إِنَّهُمۡ يَكِيدُونَ كَيۡدٗا﴿١٥

15Dájúdájú wọ́n ń déte gan-an.

وَأَكِيدُ كَيۡدٗا﴿١٦

16Èmi náà sì ń déte gan-an.[1]

فَمَهِّلِ ٱلۡكَٰفِرِينَ أَمۡهِلۡهُمۡ رُوَيۡدَۢا﴿١٧

17Nítorí náà, lọ́ra fún àwọn aláìgbàgbọ́. Lọ́ wọn lára sẹ́ fún ìgbà díẹ̀.

RELATED SURAHS