An-Nazi'at

النازعات

Those Who Drag Forth46 ayahsMeccan

بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ

وَٱلنَّٰزِعَٰتِ غَرۡقٗا﴿١

1Allāhu fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́ búra.

وَٱلنَّٰشِطَٰتِ نَشۡطٗا﴿٢

2Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo búra.

وَٱلسَّٰبِحَٰتِ سَبۡحٗا﴿٣

3Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀ búra.

فَٱلسَّٰبِقَٰتِ سَبۡقٗا﴿٤

4Ó tún fi àwọn mọlāika tó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà búra.

فَٱلۡمُدَبِّرَٰتِ أَمۡرٗا﴿٥

5Ó tún fi àwọn mọlāika tó ń ṣètò nínú sánmọ̀ àti ilé ayé pẹ̀lú àṣẹ Allāhu búra.

يَوۡمَ تَرۡجُفُ ٱلرَّاجِفَةُ﴿٦

6Ní ọjọ́ tí ìmìtìtì máa mi gbogbo ayé tìtì.[1]

تَتۡبَعُهَا ٱلرَّادِفَةُ﴿٧

7Ohun tí ó máa tẹ̀lé e máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e.[1]

قُلُوبٞ يَوۡمَئِذٖ وَاجِفَةٌ﴿٨

8Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.

أَبۡصَٰرُهَا خَٰشِعَةٞ﴿٩

9Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.

يَقُولُونَ أَءِنَّا لَمَرۡدُودُونَ فِي ٱلۡحَافِرَةِ﴿١٠

10Wọn yóò wí pé: “Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?

أَءِذَا كُنَّا عِظَٰمٗا نَّخِرَةٗ﴿١١

11Ṣé nígbà tí a ti di eegun tó kẹfun tán?”

قَالُواْ تِلۡكَ إِذٗا كَرَّةٌ خَاسِرَةٞ﴿١٢

12Wọ́n wí pé: “Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni tó pè é ní irọ́.)”

فَإِنَّمَا هِيَ زَجۡرَةٞ وَٰحِدَةٞ﴿١٣

13Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.

فَإِذَا هُم بِٱلسَّاهِرَةِ﴿١٤

14Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.

هَلۡ أَتَىٰكَ حَدِيثُ مُوسَىٰٓ﴿١٥

15Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?

إِذۡ نَادَىٰهُ رَبُّهُۥ بِٱلۡوَادِ ٱلۡمُقَدَّسِ طُوًى﴿١٦

16(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonúfojì mímọ́, Tuwā.

ٱذۡهَبۡ إِلَىٰ فِرۡعَوۡنَ إِنَّهُۥ طَغَىٰ﴿١٧

17Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-ààlà.

فَقُلۡ هَل لَّكَ إِلَىٰٓ أَن تَزَكَّىٰ﴿١٨

18Kí o sì sọ pé: “Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?

وَأَهۡدِيَكَ إِلَىٰ رَبِّكَ فَتَخۡشَىٰ﴿١٩

19Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, kí o sì páyà (Rẹ̀).”

فَأَرَىٰهُ ٱلۡأٓيَةَ ٱلۡكُبۡرَىٰ﴿٢٠

20Ó sì fi àmì tó tóbi hàn án.

فَكَذَّبَ وَعَصَىٰ﴿٢١

21(Àmọ́) ó pè é ní òpùrọ́. Ó sì yapa (rẹ̀).

ثُمَّ أَدۡبَرَ يَسۡعَىٰ﴿٢٢

22Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).

فَحَشَرَ فَنَادَىٰ﴿٢٣

23Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.

فَقَالَ أَنَا۠ رَبُّكُمُ ٱلۡأَعۡلَىٰ﴿٢٤

24Ó sì wí pé: “Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ.”

فَأَخَذَهُ ٱللَّهُ نَكَالَ ٱلۡأٓخِرَةِ وَٱلۡأُولَىٰٓ﴿٢٥

25Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).[1]

إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَعِبۡرَةٗ لِّمَن يَخۡشَىٰٓ﴿٢٦

26Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni tó ń páyà (Allāhu).

ءَأَنتُمۡ أَشَدُّ خَلۡقًا أَمِ ٱلسَّمَآءُۚ بَنَىٰهَا﴿٢٧

27Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?

رَفَعَ سَمۡكَهَا فَسَوَّىٰهَا﴿٢٨

28Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé tó gún régé.

وَأَغۡطَشَ لَيۡلَهَا وَأَخۡرَجَ ضُحَىٰهَا﴿٢٩

29Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.

وَٱلۡأَرۡضَ بَعۡدَ ذَٰلِكَ دَحَىٰهَآ﴿٣٠

30Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.[1]

أَخۡرَجَ مِنۡهَا مَآءَهَا وَمَرۡعَىٰهَا﴿٣١

31Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.

وَٱلۡجِبَالَ أَرۡسَىٰهَا﴿٣٢

32Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.

مَتَٰعٗا لَّكُمۡ وَلِأَنۡعَٰمِكُمۡ﴿٣٣

33Ìgbádùn ni fún yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.

فَإِذَا جَآءَتِ ٱلطَّآمَّةُ ٱلۡكُبۡرَىٰ﴿٣٤

34Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,

يَوۡمَ يَتَذَكَّرُ ٱلۡإِنسَٰنُ مَا سَعَىٰ﴿٣٥

35ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun tó ṣe níṣẹ́.

وَبُرِّزَتِ ٱلۡجَحِيمُ لِمَن يَرَىٰ﴿٣٦

36Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni tó ríran.

فَأَمَّا مَن طَغَىٰ﴿٣٧

37Nítorí náà, ní ti ẹni tó tayọ ẹnu-ààlà,

وَءَاثَرَ ٱلۡحَيَوٰةَ ٱلدُّنۡيَا﴿٣٨

38tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,

فَإِنَّ ٱلۡجَحِيمَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ﴿٣٩

39dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).

وَأَمَّا مَنۡ خَافَ مَقَامَ رَبِّهِۦ وَنَهَى ٱلنَّفۡسَ عَنِ ٱلۡهَوَىٰ﴿٤٠

40Ní ti ẹni tí ó páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),

فَإِنَّ ٱلۡجَنَّةَ هِيَ ٱلۡمَأۡوَىٰ﴿٤١

41dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).

يَسۡـَٔلُونَكَ عَنِ ٱلسَّاعَةِ أَيَّانَ مُرۡسَىٰهَا﴿٤٢

42Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: “Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?”

فِيمَ أَنتَ مِن ذِكۡرَىٰهَآ﴿٤٣

43Níbo ni ìwọ wà sí ìmọ̀ rẹ̀ ná?[1]

إِلَىٰ رَبِّكَ مُنتَهَىٰهَآ﴿٤٤

44Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.

إِنَّمَآ أَنتَ مُنذِرُ مَن يَخۡشَىٰهَا﴿٤٥

45Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni tó ń páyà rẹ̀.

كَأَنَّهُمۡ يَوۡمَ يَرَوۡنَهَا لَمۡ يَلۡبَثُوٓاْ إِلَّا عَشِيَّةً أَوۡ ضُحَىٰهَا﴿٤٦

46Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò gbé ilé ayé tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan.

RELATED SURAHS